Hymn 265: When God of old came down from heaven

‘Gbani t’ Olorun sokale

  1. f Gbani t’ Ọlọrun sọkalẹ,
    O wá ni ibinu;
    Ará sì nsan niwaju Rẹ̀,
    Okunkun on ina.

  2. p Nigbat’ o wá nigba keji,
    O wá ninu ifẹ;
    pp Ẹmi Rẹ̀ sì ntù ni lara,
    B’ afẹfẹ owurọ̀.

  3. f Iná Sinài ijọ kini,
    T’ọwọ rẹ̀ mbù soke,
    mp Sọkalẹ jẹjẹ bi ade,
    Si ori gbogbo wọn.

  4. f Bi ohùn ẹ̀ru na ti dún,
    L’eti Israeli,
    Ti nwọn si gbọ iró ipè,
    To m’ohùn angẹl gbọ̀n.

  5. mf Bẹ gẹgẹ nigbat’ Ẹmi wá
    Bà le awọn Tirẹ̀,
    cr Iró kan si ti ọrun wa,
    Iró iji lile.

  6. f O nkun Ijọ Jesu, o nkun
    Aiye ẹsẹ yika;
    mp L’ọkàn alaigbọràn nikan
    Ni àye kò si fun.

  7. mf Wa, Ọgbọn, Ifẹ, at’ Ipa,
    Mu ki eti wa ṣí;
    p K’a má sọ akoko wa nù;
    Ki ‘fẹ Rẹ le gbà wa. Amin.